Ijó Leader (Live)-文本歌词

Ijó Leader (Live)-文本歌词

K1 De Ultimate
发行日期:

Ijó wá dijó leader gbogbo

Latest Leader gbogbo Lagos State

Abdullahi Ẹnílọlóbọ̀ àti àwọn leader tó kù pátápátá

Usamat máa wolẹ̀ máa ràba

Shehu, o ṣeun mi

Ṣé ò ń bá mi tọ́jú Usamat Honourable Commissioner for Social Development and Youth

Gbogbo yín ni mo kí pátápátá

Alimosho Area ìkan ṣoṣo ni, lẹ fi kó gbogbo ilé pọ̀, ló fi dìkan

Kò ní bàjẹ́ lọ́lá Ọlọ́hun Ọba

Fẹ́mi, member Federal House of Representative ọmọ Adébájọ

Honourable Bísí ọmọ Yusufu mi o member, Lagos State House of Assembly

Àti Abudulahi ọmọ t’ẹní lọ ló bọ̀ ọkọ Shukurah, ọkọ Abibat mi

Woman leader ẹgbẹ́ wa máa wolẹ̀ máa ràba

Chief Mrs Kẹ́mi Nelson, o kú oríire, ọ̀rọ̀ social insurance ó jẹ wá lógún

Ìyẹn wá ń bẹ lọ́wọ́ wa báyìí, Buhari ti fún wa láṣẹ ko ma pàṣẹ lọ

Ọlọ́hun á fun yín ṣe ò, ọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà o

Àwọn gbẹ̀yìnbẹbọjẹ́, wọ́n ń bẹbọjẹ́ fún wa Wasiu Àyìndé

Latest Leader máa wolẹ̀ máa ràba Abudulahi mi

Alhaji Isah Yusufu mi o, latest leader

YY gbogbo ara ni mo fi kí ẹ o ọmọ Yusufu mi

Ọkọ Modúpẹ́ọlá mi ọkọ Modúpẹ́

Gbogbo yín ẹ kú àdúrótì o

Alimosho Day, 2017

Gbogbo ẹ̀yin leader, mo ki yín o Àyìndé o

Woman leader nínú ẹgbẹ́ wa

Bólọ́hun bá ṣògo o, ó yẹ ká dúpẹ́

(Woman leader nínú ẹgbẹ́ wa)

(Bólọ́hun bá ṣògo o, ó yẹ ká dúpẹ́)

Chief Mrs Kẹ́mi Nelson, etí inú

Gbogbo ẹbí lékòó pátápátá

Lókè pòpó, ní ilé Tinubu ní Kakawa

Woman Leader Ẹgbẹ́ wa o, dé gbogbo South West

Chief Mrs Kẹ́mi Nelson mi

Ìyàwó Nelson mi Kẹ́mi baby mi

Chief Mrs, o mà kú oríire

Béèyàn bá gba Federal appointment Àyìndé Ọmọ́gbọ́láhàn

9 yẹ ká ba jó

Woman leader nínú ẹgbẹ́ wa

Bólọ́hun bá ṣògo o, ó yẹ ká dúpẹ́

(Woman leader nínú ẹgbẹ́ wa)

(Bólọ́hun bá ṣògo o, ó yẹ ká dúpẹ́)

Ẹ̀dá tí ò bá dúpẹ́ oore Ọlọ́run Ọba o

Ó dàbí abara móore jẹ ni o

Bẹ́ẹ bá fun ni ohun tó pọ̀ jù bẹ́ẹ̀

Kò ní dúpẹ́ Ọmọ́gbọ́láhàn ó yẹ ká dúpẹ́ Oore

Bó ti lè wù kó mọ bíntín

Oore Ọlọ́hun Ọba ni

Lágbára Ọlọ́hun Ọba lásìkò tì ẹ ó máa ṣe àṣeyọrí

O ti ṣe tẹ́lẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí

Àyìndé ní Lagos State, ṣé ẹ ní etí

Ó ti ṣe plenty plenty rí ní Lagos State

Chief Mrs Nelson, opportunity kan rè é fún gbogbo Nàìjíríà

Ẹ jẹ́ kí Abudulahi, ẹ jẹ́ ó dílé mú

Á máa lọ á máa bọ̀, ẹ jẹ́ ó ìdílé mú

Ló fi jẹ́ Apex, tí wọ́n bá p’èèyàn ní Apex Leader

Ilé lọ́wọ́ ẹ ló wà, Abdullahi ló ìdílé mú

Chief Mrs Kẹ́mi Nelson, Buhari ti fún ẹ láṣẹ o ò ri bí

Ọ̀rọ̀ Social Insurance NÍ gbogbo Nàìjíríà

K’áwa náà ká lọ ṣe tiwa níbẹ̀, ká le ṣe àṣeyọrí

Kẹ́mi Ọlọ́hun á bá ẹ (Ọlọ́hun á bá ẹ ṣé)

Eh!

Woman leader gbogbo South West

Oyè púpọ̀ ló kó dání, ó kó South West ó ko dání

Ó mú Lagos State, ó ko dání

Ó tún mú Federal, ó tún mu dání

Gbogbo ẹ̀ gbògbò ẹ̀ lọ́wọ́ Àkànbí ọmọ Olódó idẹ o

Kú lé mi ò tún gbọ́dọ̀ pè ẹ́ mọ́

Adúpẹ́ lọ́wọ́ leader Aṣíwájú

Ibi téèyàn bá ṣe sí ló ti ń jẹ Àyìndé mi Gbọ́láhàn o

Nígbà téèyàn ń ṣe ọmọ ẹgbẹ́, Chief Mrs Kẹ́mi Kẹ́mi

O ṣe ohun ẹgbẹ́ gidi

Ìgbà tó tún di leader, tó tún jẹ́ olórí

O tún ilé ṣe, tún ọ̀nà ṣe, o tọ́jú ará

Kẹ́mi Nelson, o tọ́jù ẹbí

Adúpẹ́ fún Ọlọ́hun Ọba, èyí ò tíì tó

Bó bá jẹ Minister nílẹ̀ yìí kò mà pọ̀ àpọ̀ jù

Ṣùgbọ́n, ẹsẹ̀ kan là á gbé kátó gbé ìkan ò Àyìndé mi Gbọ́láhàn o